2 Chronicles 19:11 — Compare Translations
3 translations compared side by side
Yoruba 2010
Amaraya, olórí alufaa ni alabojuto yín ninu gbogbo nǹkan tí ó bá jẹ mọ́ OLUWA. Sebadaya, ọmọ Iṣimaeli, tí ó jẹ́ gomina ní Juda ni alabojuto lórí ọ̀rọ̀ ìlú, àwọn ọmọ Lefi yóo sì máa ṣe òjíṣẹ́ yín. Ẹ má bẹ̀rù. Kí OLUWA wà pẹlu ẹ̀yin tí ẹ dúró ṣinṣin.”
Yoruba YBCV (Bibeli Mimọ)
Si wõ, Amariah, alufa ni olori lori nyin ni gbogbo ọ̀ran Oluwa; ati Sebadiah, ọmọ Iṣmaeli, alakoso ile Juda, fun ọ̀ran ọba; pẹlupẹlu ẹnyin ni olutọju awọn ọmọ Lefi pẹlu nyin. Ẹ mu ara le, ki ẹ si ṣe, Oluwa yio pẹlu ẹni-rere.
Yoruba YCB (Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní)
“Ámáríyà àlùfáà ni yóò jẹ́ olórí yín nínú gbogbo ọ̀ràn tí ó jẹ́ ti OLÚWA, àti Ṣébádíà ọmọ Íṣímáélì alákòóso ìdílé Júdà, ní yóò jẹ́ olórí ní gbogbo ọ̀rọ̀ tí ọba, àti àwọn ará Léfì pẹ̀lu yin yóò sìn gẹ́gẹ́ bí ìjòyè níwájú yín. Ẹ ṣeé pẹ̀lú ìmọ́kànle, OLÚWA yóò sì wà pẹ̀lú àwọn tó bá ń ṣe rere.”