2 Chronicles 24:6 — Compare Translations

3 translations compared side by side

Yoruba 2010
Nítorí náà, ọba ranṣẹ pe Jehoiada tí ó jẹ́ olórí wọn, ó bèèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé: “Kí ló dé tí ẹ kò fi jẹ́ kí àwọn ọmọ Lefi lọ máa gba owó fún àgọ́ ẹ̀rí lọ́wọ́ àwọn eniyan Juda ati Jerusalẹmu bí Mose, iranṣẹ OLUWA, ti pa á láṣẹ?”
Yoruba YBCV (Bibeli Mimọ)
Ọba si pè Jehoiada, olori, o si wi fun u pe, Ẽṣe ti iwọ kò bère li ọwọ awọn ọmọ Lefi, ki nwọn ki o mu owo ofin Mose, iranṣẹ Oluwa, lati Juda ati lati Jerusalemu wá, ati ti ijọ-enia Israeli fun agọ ẹri?
Yoruba YCB (Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní)
Nítorí náà ọba paálásẹ fún Jéhóiádà olorí àlùfáà ó sì wí fún-un pé, “Kí ni ó dé tí o kò, bèèrè lọ́wọ́ àwọn ará Léfì láti mú wá láti Júdà àti Jérúsálẹ́mù, owó orí tí Mósè ìránṣẹ́ OLÚWA ti fi lélẹ̀ àti nípasẹ̀ àpéjọ gbogbo Ísírẹ́lì fún àgọ́ ìjẹ́rìí?”