2 Chronicles 7:3 — Compare Translations

3 translations compared side by side

Yoruba 2010
Nígbà tí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli rí i bí iná ati ògo OLUWA ti sọ̀kalẹ̀ sórí tẹmpili, wọ́n dojúbolẹ̀, wọ́n sin Ọlọrun, wọ́n fi ọpẹ́ fún un, “Nítorí pé ó ṣeun, nítorí pé àánú rẹ̀ wà títí lae.”
Yoruba YBCV (Bibeli Mimọ)
Gbogbo awọn ọmọ Israeli si ri bi iná na ti bọ́ silẹ, ati ogo Oluwa sori ile na, nwọn doju wọn bò ilẹ ti a fi okuta tẹ́, nwọn si tẹriba, nwọn si yìn Oluwa, wipe, Nitoriti o ṣeun; nitoriti ãnu rẹ̀ duro lailai.
Yoruba YCB (Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní)
Nígbà tí gbogbo àwọn ọmọ Ísírẹ́lì rí iná tí ó ń sọ̀kalẹ̀ àti ògo OLÚWA lórí ilé OLÚWA náà, wọ́n sì kúnlẹ̀ lórí eékún wọn pẹ̀lú ojú wọn dídàbolẹ̀, wọ́n sì sin OLÚWA, wọ́n sì fi ìyìn fún OLÚWA wí pé, “Nítorí tí ó dára; àánú rẹ̀ sì dúró títí láéláé.”