bible
ra
🌐 Language
English
Español
Français
Deutsch
Português
Italiano
Nederlands
Русский
中文
日本語
한국어
العربية
Türkçe
Tiếng Việt
ไทย
Indonesia
All Languages
Home
/
Yoruba
/
Yoruba YCB (Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní)
/
2 Chronicles 7
2 Chronicles 7
Yoruba YCB (Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní)
← Chapter 6
Jump to:
Chapter 1
Chapter 2
Chapter 3
Chapter 4
Chapter 5
Chapter 6
Chapter 7
Chapter 8
Chapter 9
Chapter 10
Chapter 11
Chapter 12
Chapter 13
Chapter 14
Chapter 15
Chapter 16
Chapter 17
Chapter 18
Chapter 19
Chapter 20
Chapter 21
Chapter 22
Chapter 23
Chapter 24
Chapter 25
Chapter 26
Chapter 27
Chapter 28
Chapter 29
Chapter 30
Chapter 31
Chapter 32
Chapter 33
Chapter 34
Chapter 35
Chapter 36
Chapter 8 →
1
Nígbà tí Sólómónì sì ti parí àdúrà, iná sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run ó sì jó ọrẹ sísun àti ẹbọ, ògo Ọlọ́run sì kún ilé OLÚWA.
2
Àwọn àlùfáà wọn kò sì le wo ilé OLÚWA náà nítorí pé ògo OLÚWA kún un.
3
Nígbà tí gbogbo àwọn ọmọ Ísírẹ́lì rí iná tí ó ń sọ̀kalẹ̀ àti ògo OLÚWA lórí ilé OLÚWA náà, wọ́n sì kúnlẹ̀ lórí eékún wọn pẹ̀lú ojú wọn dídàbolẹ̀, wọ́n sì sin OLÚWA, wọ́n sì fi ìyìn fún OLÚWA wí pé, “Nítorí tí ó dára; àánú rẹ̀ sì dúró títí láéláé.”
4
Nígbà náà ọba àti gbogbo àwọn ènìyàn sì rú ẹbọ níwájú OLÚWA.
5
Ọba Sólómónì sì rúbọ ọrẹ ti ẹgbà á mọ́kànlá (22,000), orí màlúù àti àgùntàn àti ọkẹ́ mẹ́fà àgùntàn àti ẹranko. Bẹ́ẹ̀ ni ọba àti gbogbo àwọn ènìyàn ya ilé Ọlọ́run sí mímọ́.
6
Àwọn àlùfáà dúró ní àyè wọn, gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Léfì ti ṣe pẹ̀lú ohun èlò orin OLÚWA, tí ọba Dáfídì ti ṣe fún ìyìn OLÚWA àti tí á lò nígbà tí ó dúpẹ́, wí pé, “àànú rẹ̀ sì dúró láéláé,” níwájú àwọn ọmọ Léfì, àwọn àlùfáà sì fọn ipè, gbogbo àwọn ọmọ Ísírẹ́lì sì dúró.
7
Sólómónì sì yà sọ́tọ̀ láàrin àgbàlá níwájú ilé OLÚWA, níbẹ̀ sì ni ó ti se ìrúbọ ọrẹ sísun àti ọ̀rá ẹbọ àlàáfíà, nítorí pẹpẹ idẹ tí ó ti ṣe kò lè gba ọrẹ sísun, àti ọrẹ oúnjẹ, àti ọ̀rá náà.
8
Bẹ́ẹ̀ ni Sólómónì se àsè ní àkókò náà fún ọjọ́ méje àti gbogbo àwọn ọmọ Ísírẹ́lì pẹ̀lú rẹ̀ àti ìjọ ènìyàn ńlá, àwọn ènìyàn láti Lébò Hámátì títí dé odò Éjíbítì.
9
Ní ọjọ́ kẹ́jọ, wọ́n sì pe ìjọ ènìyàn jọ nítorí tí wọ́n pe àpèjẹ ìyà símímọ́ ti orí pẹpẹ fún ọjọ́ méje àti àṣe náà fún ọjọ́ méje sí i.
10
Ní ọjọ́ kẹtàlélógún (23rd day) tí oṣù kéje, ó sì rán àwọn ènìyàn padà sí ilé wọn, pẹ̀lú ayọ̀ àti ìdùnnú nínú wọn fún ohun rere tí OLÚWA ti ṣe fún Dáfídì àti Sólómónì, àti fún àwọn ènìyàn Ísírẹ́lì.
11
Nígbà tí Sólómónì ti parí ilé OLÚWA àti ibi ilé ọba, nígbà tí ó sì ti ṣe àṣeyọrí láti gbé jáde gbogbo ohun tí ó ní lọ́kàn láti ṣe nínú ilé OLÚWA àti nínú ilé òun tìkálárarẹ̀,
12
OLÚWA sì farahàn ní òru ó sì wí pé: “Èmi ti gbọ́ àdúrà rẹ mo sì ti yàn ibííyí fún ara mi gẹ́gẹ́ bí ilé fún ẹbọ.
13
“Nígbà tí mo bá sé ọ̀run kí ó ma báà sí òjò, tàbí láti pàsẹ fún eṣú láti jẹ ilẹ̀ náà run tàbí rán àjàkálẹ̀-àrùn sí àárin àwọn ènìyàn mi,
14
Tí àwọn ènìyàn, tí a fi orúkọ mi pè, tí wọ́n bá rẹ ara wọn sílẹ̀, tí wọ́n sì gbàdúrà, tí wọ́n sì rí ojú mi, tí wọ́n sì yí kúrò nínú ọ̀nà búburú wọn, nígbà náà, èmi yóò gbọ́ láti ọ̀run, èmi yóò sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ wọn jìn wọ́n èmi yóò sì wo ilẹ̀ wọn sàn.
15
Nísisinyí, ojú mi yóò sì là etí mi yóò sì là, sí àdúrà ọrẹ níbíyìí.
16
Èmi sì ti yàn, èmi sì ti ya ilé yìí sí mímọ́ bẹ́ẹ̀ ni kí orúkọ mi kí ó le wà níbẹ̀ títí láéláé.
17
“Ní ti bí ìwọ bá rìn níwájú mi gẹ́gẹ́ bí Dáfídì baba rẹ ti ṣe, tí o sì ṣe gbogbo ohun tí mo palásẹ, tí ìwọ sì ṣe àkíyèsí àṣẹ mi láti ọ̀run:
18
Èmi yóò fi ìdí ìtẹ́ ìjọba rẹ múlẹ̀, gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe pẹ̀lú Dáfídì baba rẹ nígbà tí mo bá a dá májẹ̀mu wí pé, ìwọ kò ní fẹ́ ẹnìkan kù láti ṣe alákòóso lórí Ísírẹ́lì.
19
“Ṣùgbọ́n tí ìwọ bá yípadà tí o sì kọ òfin mi sílẹ̀ àti àṣẹ tí mo ti fi fún yín tí ẹ sì lọ sókè láti lọ sin Ọlọ́run mìíràn tí ẹ sì bọ wọ́n,
20
Nígbà náà ni èmi yóò fa Ísírẹ́lì tu kúrò láti ilẹ̀ mi, èyí tí èmi ti fi fún wọn, èmi yóò sì kọ̀ ilé náà sílẹ̀ èyí tí èmi ti yà sọ́tọ̀ fún orúkọ mi, èmi yóò sì fi ṣe ọ̀rọ̀ òwe, n ó fi ṣe ẹlẹ́yà láàrin gbogbo ènìyàn,
21
Àti ní gbogbo àyíká ilé yìí nísinsinyí, bẹ́ẹ̀ ni yóò di ohun ìtànjẹ; gbogbo àwọn tí ó bá sì kọjá níbẹ̀ ni yóò jáláyà, wọn yóò sì wí pé, ‘Kí ni ó dé tí OLÚWA fì ṣe irú èyí sí ilẹ̀ yí àti sí ilé yìí?’
22
Àwọn ènìyàn yóò sì dáhùn wí pé: ‘Nítorí tí wọ́n ti kọ̀ OLÚWA sílẹ̀, Ọlọ́run baba wọn ẹni tí ó mú wọn jáde láti Éjíbítì wá, wọ́n sì ti fi ọwọ́ gba Ọlọ́run mìíràn mọ́ra, wọ́n bọ wọ́n, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ń sìn wọ́n, ìdí nìyí tí ó fi mú gbogbo ìjàǹbá náà wá sórí wọn.’ ”
← Chapter 6
Jump to:
Chapter 1
Chapter 2
Chapter 3
Chapter 4
Chapter 5
Chapter 6
Chapter 7
Chapter 8
Chapter 9
Chapter 10
Chapter 11
Chapter 12
Chapter 13
Chapter 14
Chapter 15
Chapter 16
Chapter 17
Chapter 18
Chapter 19
Chapter 20
Chapter 21
Chapter 22
Chapter 23
Chapter 24
Chapter 25
Chapter 26
Chapter 27
Chapter 28
Chapter 29
Chapter 30
Chapter 31
Chapter 32
Chapter 33
Chapter 34
Chapter 35
Chapter 36
Chapter 8 →
All chapters:
1
2
3
4
5
6
7
8
9
10
11
12
13
14
15
16
17
18
19
20
21
22
23
24
25
26
27
28
29
30
31
32
33
34
35
36