bible
ra
🌐 Language
English
Español
Français
Deutsch
Português
Italiano
Nederlands
Русский
中文
日本語
한국어
العربية
Türkçe
Tiếng Việt
ไทย
Indonesia
All Languages
Home
/
Yoruba
/
Yoruba YCB (Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní)
/
Job 39
Job 39
Yoruba YCB (Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní)
← Chapter 38
Jump to:
Chapter 1
Chapter 2
Chapter 3
Chapter 4
Chapter 5
Chapter 6
Chapter 7
Chapter 8
Chapter 9
Chapter 10
Chapter 11
Chapter 12
Chapter 13
Chapter 14
Chapter 15
Chapter 16
Chapter 17
Chapter 18
Chapter 19
Chapter 20
Chapter 21
Chapter 22
Chapter 23
Chapter 24
Chapter 25
Chapter 26
Chapter 27
Chapter 28
Chapter 29
Chapter 30
Chapter 31
Chapter 32
Chapter 33
Chapter 34
Chapter 35
Chapter 36
Chapter 37
Chapter 38
Chapter 39
Chapter 40
Chapter 41
Chapter 42
Chapter 40 →
1
“Ìwọ mọ àkókò ìgbà tíàwọn ewúrẹ́ orí àpáta ìbímọ? Ìwọ sì lè kíyèsí ìgbà tí abo àgbọ̀nrín ń bímọ?
2
Ìwọ lè ka iye òṣùpá tí wọn ń pè, ìwọ sì mọ àkókò ìgbà tí wọn ń bímọ,
3
Wọ́n tẹ ara wọn ba, wọ́n bí mọ, wọ́n sì mú ìkáànú wọn jáde.
4
Àwọn ọmọ wọn rí dáradára, wọ́n dàgbà nínú ọ̀dàn; wọ́n jáde lọ, wọn kò sì tún padà wá sọ́dọ̀ wọn.
5
“Ta ni ó jọ̀wọ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ oko lọ́wọ́? Tàbí ta ní ó tú ìdè kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ìgbẹ́,
6
Èyí tí mo fi ihà ṣe ilé fún, àti ilẹ̀ iyọ̀ ní ibùgbé rẹ̀
7
Ó rẹ́rìnín sí ariwo ìlú, bẹ́ẹ̀ ni Òun kò sì gbọ́ igbe darandaran.
8
Orí àtòlé òkè ńlá ni ibùjókòó rẹ̀, Òun asì má a wá ewé tútù gbogbo rí.
9
“Àgbáǹréré ha jẹ́ sìn ọ́ bí? Tàbí, ó jẹ́ dúró ní ibùjẹ ẹran rẹ ní òru?
10
Ìwọ le fi òkò tata de àgbáǹréré nínú aporo? Tàbí ó jẹ́ máa fa ìtulẹ̀ nínú aporo oko tọ̀ ọ́ lẹ́yìn?
11
Ìwọ ó gbẹ́kẹ̀ lée nítorí agbára rẹ̀ pọ̀ ìwọ ó sì fi iṣẹ́ rẹ lé e lọ́wọ́?
12
Ìwọ le gbẹ́kẹ̀ le pé, yóò mú èso oko rẹ̀ wá sílé, àti pé yóò sì kó ọ jọ sínu àká rẹ?
13
“Ìyẹ́ abo ògòǹgò ń fi ayọ̀ fì; Ṣùgbọ́n a kò le fi àká we ara wọn ní ìyẹ́ àti ìhùhù
14
Ó yé ẹ̀yìn rẹ̀ sílẹ̀ lórí ilẹ̀, a sì mú wọn gbóná nínú ekuru;
15
Tí ó sì gbàgbé pé, ẹ̀sẹ̀ lè tẹ̀ wọ́n fọ́, tàbí pé ẹranko ìgbẹ́ lè tẹ̀ wọ́n fọ́.
16
Kò ní àánú sí àwọn ọmọ rẹ̀ bí ẹni pé wọn kì í ṣe tirẹ̀; asán ni iṣẹ́ rẹ̀, láì ní ìbẹ̀rù;
17
Nítorí pé Ọlọ́run kò fún-un ní ọgbọ́n, bẹ́ẹ̀ ni kò sì fi ìpín òye fún un.
18
Nígbà tí ó gbé ara sókè, ó gan ẹṣin àti ẹlẹ́ṣin.
19
“Ìwọ ni ó fi agbára fún ẹṣin bí? tàbí ṣé Ìwọ ni ó fi gọ̀gọ̀ wọ ọrùn rẹ̀ ní aṣọ?
20
Ìwọ le mú fò sókè bí ẹlẹ́ǹgà? Ògo èémí imú rẹ ní ẹ̀rù ńlá;
21
Ó fi ẹsẹ̀ halẹ̀ nínú àfonífojì, ó sì yọ̀ sí agbára rẹ̀; ó lọ jáde láti pàdé àwọn ìhámọ́ra ogun.
22
Ó fi ojú kékeré wo ẹ̀rù, àyà kò sì fòó; bẹ́ẹ̀ ni kì í sì í padà ṣẹ́yìn kúrò lọ́wọ́ idà.
23
Lọ́dọ̀ rẹ ni apó-ọfà ń mì pẹ́kẹ́pẹ́kẹ́, àti ọ̀kọ̀ dídán àti àpáta.
24
Ó fi kíkorò ojú àti ìbínú ńlá gbé ilẹ̀ mì, bẹ́ẹ̀ ni òun kò sì gbàá gbọ́ pé, ìró ipè ni.
25
Ó wí nígbà ìpè pé, Háà! Háà! Ó sì gbóhùn ogun lókè réré, ara àwọn balógun àti ariwo ogun wọn.
26
“Àwòdì ha máa ti ipa ọgbọ́n rẹ̀ fò sókè tí ó sì mọ ìyẹ́ apá rẹ̀ sí ìhà gúsù?
27
Idì ha máa fi àṣẹ rẹ̀ fò sókè kí ó sì lọ tẹ́ ìtẹ́ rẹ̀ sí òkè gíga?
28
Ó ń gbé, ó sì ń wò ní orí àpáta, lórí pàlàpálá òkúta àti ibi orí òkè.
29
Láti ibẹ̀ lọ ni ó ti ń wá oúnjẹ́ kiri, ojú rẹ̀ sì ríran rí òkè réré.
30
Àwọn ọmọ rẹ̀ pẹ̀lú a máa mu ẹ̀jẹ̀, níbi tí òkú bá gbé wà, níbẹ̀ ni òun wà pẹ̀lú.”
← Chapter 38
Jump to:
Chapter 1
Chapter 2
Chapter 3
Chapter 4
Chapter 5
Chapter 6
Chapter 7
Chapter 8
Chapter 9
Chapter 10
Chapter 11
Chapter 12
Chapter 13
Chapter 14
Chapter 15
Chapter 16
Chapter 17
Chapter 18
Chapter 19
Chapter 20
Chapter 21
Chapter 22
Chapter 23
Chapter 24
Chapter 25
Chapter 26
Chapter 27
Chapter 28
Chapter 29
Chapter 30
Chapter 31
Chapter 32
Chapter 33
Chapter 34
Chapter 35
Chapter 36
Chapter 37
Chapter 38
Chapter 39
Chapter 40
Chapter 41
Chapter 42
Chapter 40 →
All chapters:
1
2
3
4
5
6
7
8
9
10
11
12
13
14
15
16
17
18
19
20
21
22
23
24
25
26
27
28
29
30
31
32
33
34
35
36
37
38
39
40
41
42