bible
ra
🌐 Language
English
Español
Français
Deutsch
Português
Italiano
Nederlands
Русский
中文
日本語
한국어
العربية
Türkçe
Tiếng Việt
ไทย
Indonesia
All Languages
Home
/
Yoruba
/
Yoruba YCB (Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní)
/
Proverbs 10
Proverbs 10
Yoruba YCB (Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní)
← Chapter 9
Jump to:
Chapter 1
Chapter 2
Chapter 3
Chapter 4
Chapter 5
Chapter 6
Chapter 7
Chapter 8
Chapter 9
Chapter 10
Chapter 11
Chapter 12
Chapter 13
Chapter 14
Chapter 15
Chapter 16
Chapter 17
Chapter 18
Chapter 19
Chapter 20
Chapter 21
Chapter 22
Chapter 23
Chapter 24
Chapter 25
Chapter 26
Chapter 27
Chapter 28
Chapter 29
Chapter 30
Chapter 31
Chapter 11 →
1
Àwọn òwe Sólómónì: Ọlọgbọ́n ọmọ ń mú inú baba rẹ̀ dùn ṣùgbọ́n aláìgbọ́n ọmọ ń ba inú ìyá rẹ̀ jẹ́.
2
Ìṣúra tí a kójọ nípa ìwà búburú kò ní èrè ṣùgbọ́n òdodo a máa gbani lọ́wọ́ ikú.
3
OLÚWA kì í jẹ́ kí ebi máa pa Olódodo ṣùgbọ́n ó ba ète àwọn ènìyàn búburú jẹ́.
4
Ọwọ́ tí ó lẹ máa ń sọ ènìyàn di talákà, ṣùgbọ́n ọwọ́ tí ó múra síṣẹ́ a máa sọni di ọlọ́rọ̀.
5
Ẹni tí ó kó irúgbìn jọ ní àsìkò òjò jẹ́ Ọlọ́gbọ́n ọmọ, ṣùgbọ́n ẹni tí ó sùn ní àsìkò ìkórè jẹ́ adójútini ọmọ.
6
Ìbùkún ní ó máa ń kún orí Olódodo ṣùgbọ́n ìwà ipá máa ń kún ẹnu ènìyàn búburú.
7
Ìrántí Olódodo yóò jẹ́ ìbùkún ṣùgbọ́n orúkọ ènìyàn búburú yóò jẹrà.
8
Ẹni tí ó gbọ́n nínú ọkàn rẹ̀ máa ń gba àṣẹ ṣùgbọ́n ètè wérewère yóò parun.
9
Ẹni oníwà títọ́ ń rìn láìléwu ṣùgbọ́n àsírí ẹni tí ń rin ọ̀nà pálapàla yóò tú.
10
Ẹni tí ń sẹ́jú pàkòpàkò fún ibi ń fa àìbalẹ̀ ọkàn Aláìgbọ́n tí ń ṣàròyé kiri yóò parun.
11
Ẹnu Olódodo jẹ́ oríṣun ìyè ṣùgbọ́n ìwà ipá ni ó gba gbogbo ẹnu ènìyàn búburú.
12
Ìríra a máa dá ìjà sílẹ̀, ṣùgbọ́n ìfẹ́ a máa bo gbogbo àṣìṣe mọ́lẹ̀.
13
Ọgbọ́n ni a ń bá lẹ́nu àwọn olóye ṣùgbọ́n kùmọ wà fún ẹ̀yìn àwọn aláìlóye.
14
Ọlọ́gbọ́n ènìyàn kó ìmọ̀ jọ ṣùgbọ́n ẹnu aláìgbọ́n a máa ṣokùnfà ìparun.
15
Ọrọ̀ àwọn Olódodo ni ìlú olódi wọn, ṣùgbọ́n òsì ni ìparun aláìní.
16
Èrè Olódodo ń mú ìyè wá fún wọn ṣùgbọ́n èrè ènìyàn búburú ń mú ìjìyà wá fún wọn.
17
Ẹni tí ó gbọ́ ìbáwí fi ọ̀nà sí ìyè hàn ṣùgbọ́n ẹni tí ó kọ ìbáwí mú àwọn mìíràn sìnà.
18
Ẹni tí ó pa ìkórìíra rẹ̀ mọ́ jẹ́ òpùrọ́ ẹni tí ó sì ń báni jẹ́ jẹ́ aláìgbọ́n.
19
Nínú ọ̀rọ̀ púpọ̀ a kò le fẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ kù ṣùgbọ́n ẹni tí ó pa ẹnu rẹ̀ mọ́ jẹ́ ọlọ́gbọ́n.
20
Ètè Olódodo jẹ́ àṣàyan fàdákà ṣùgbọ́n ọkàn ènìyàn buburú kò níye lórí.
21
Ètè Olódodo ń bọ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀ ṣùgbọ́n aláìgbọ́n ń kú nítorí àìlóye.
22
Ìbùkún OLÚWA ń mú ọrọ̀ wá, kì í sìí fi ìdàámú sí i.
23
Aláìgbọ́n a máa ní inú dídùn sí ìwà búburú ṣùgbọ́n olóye ènìyàn a máa ní inú dídùn sí ọgbọ́n.
24
Ohun tí ènìyàn búburú bẹ̀rù yóò dé bá a; Olódodo yóò rí ohun tí ó fẹ́ gbà.
25
Nígbà tí ìjì bá ti jà kọjá, ènìyàn búburú a kọjá lọ, ṣùgbọ́n Olódodo yóò dúró ṣinṣin láéláé.
26
Bí ọtí kíkan sí eyín, àti èéfín sí ojú bẹ́ẹ̀ ni ọ̀lẹ sí ẹni tí ó rán an níṣẹ́.
27
Ìbẹ̀rù OLÚWA ń mú ọjọ́ ayé gígùn wá, ṣùgbọ́n a gé ojọ́ ayé ènìyàn búburú kúrú.
28
Ìrètí Olódodo ni ayọ̀ ṣùgbọ́n ìrètí ènìyàn buburú já sí òfo.
29
Ọ̀nà OLÚWA jẹ́ ààbò fún Olódodo, ṣùgbọ́n ìparun ni ó jẹ́ fún àwọn tí ń se ibi.
30
A kì yóò fa Olódodo tu láéláé ṣùgbọ́n ènìyàn buburú kì yóò dúró pẹ́ lórí ilẹ̀.
31
Ẹnu Olódodo ń mú ọgbọ́n jáde wá, ṣùgbọ́n ètè àyípadà ni a ó gé kúrò.
32
Ètè Olódodo mọ ohun tí ó tọ́, ṣùgbọ́n ètè ènìyàn búburú kò mọ̀ ju èké lọ.
← Chapter 9
Jump to:
Chapter 1
Chapter 2
Chapter 3
Chapter 4
Chapter 5
Chapter 6
Chapter 7
Chapter 8
Chapter 9
Chapter 10
Chapter 11
Chapter 12
Chapter 13
Chapter 14
Chapter 15
Chapter 16
Chapter 17
Chapter 18
Chapter 19
Chapter 20
Chapter 21
Chapter 22
Chapter 23
Chapter 24
Chapter 25
Chapter 26
Chapter 27
Chapter 28
Chapter 29
Chapter 30
Chapter 31
Chapter 11 →
All chapters:
1
2
3
4
5
6
7
8
9
10
11
12
13
14
15
16
17
18
19
20
21
22
23
24
25
26
27
28
29
30
31